27/08/2026
*ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸTÀDÍNLỌ́GBỌ̀N OṢÙ KẸ́JỌ ỌDÚN 2026*
1. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ BÍLÍỌ̀NÙ LỌ́NÀ ẸGBẸ̀TA NÁÍRÀ ( ) NI WỌ́N SAN FÚN ÀWỌN ẸBÍ TÓ TÓ MÍLÍỌ̀NÙ MẸ́WÀÁ TÓ KU DÍẸ̀ KÁÀ TÓ FÚN LÁÀRÍN ỌDÚN MẸ́TA*
2. *ÀJỌ ICRC TI ṢE ÀKỌSÍLẸ̀ Ẹ̀ PÉ ÀWỌN ẸGBẸ̀RÚN MẸ́TA ÈNÌYÀN (3,000) NI WỌ́N Ń WÁ NÍ ÌPÍNLẸ̀ NASARAWA LÉYÌÍ TÍ WỌ́N Ń WÁ ẸGBẸ̀RÚN MẸ́TÀDÍNLÓGÚN ÈNÌYÀN (17,000) NÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ*
3. *ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC) TI BÉÈRÈ FÚN NÍ NAWỌ́ GÁN ALÁGA KÁŃSÙ KÙJÉ ÌYẸN SAMUEL SHEKWOLO LÁTÀRI BÓ ṢE Ń DÚNKOKÒ PÉ KÍ ÀWỌN TÍ KÒ ṢE ÀTÌLẸ́YÌN FÚN ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC) KÚRÒ NÍ OLÚ ÌLÚ WA ÀBÚJÁ*
4. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI BÉÈRÈ FÚN WÍWỌ́GI LÉ ÀDÉHÙN ÀTÚNṢE ÒPÓPÓNÀ BENIN SÍ ÀSÀBÀ*
5. *ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PÀÁ ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀YỌ́ TI NAWỌ́ GÁN ÀWỌN AFURASÍ MẸ́WÀÁ KAN TÍ WỌ́N Ń ṢE ÒWÒ KÁRÀKÁTÀ ẸRAN ỌMỌ ÈNÌYÀN*
6. *MALAMI TI YAN ÀWỌN ÈNÌYÀN TÍ WỌ́N TÓ ẸGBẸ̀TA (600) GẸ́GẸ́ BÍ ÌGBÌMỌ̀ IKỌ̀ OLÙPOLONGO ÌBÒ FÚN ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC) NÍ ÌPÍNLẸ̀ KEBBI*
7. *ÀLHÁJÌ ABDULWAHEED AKÍNTỌ́LÁ ỌLÁJÍDÉ TÍ Ó TI FÌGBÀ KAN RÍ JẸ́ AKỌ̀WÉ FÚN ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀YỌ́, TÍ Ó SÌ TÚN JẸ́ OLÓYÈ ŃLÁ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC) TI DÁGBÉRE FÁYÉ*
8. *ONÍṢÈGÙN ÒYÌNBÓ KAN TÓ JẸ́ AKỌ́ṢẸ́MỌṢẸ́ NÍPA OJÚ TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÀWỌN ỌMỌ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TÍ WỌ́N TÓ MÍLÍỌ̀NÙ MÉJÌ NI WỌ́N Ń GBÉ PẸ̀LÚ OJÚ FÍFỌ́ TÍ WỌ́N LÈ YẸRA FÚN*
9. *ORÍLẸ̀ ÈDÈ ISRAEL TI FÚN ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ NÍ IPELE ÀKỌ́KỌ́ ÀWỌN ỌKỌ̀ PÀJÁWÌRÍ TÍ WỌ́N FI Ń KÓ ÀWỌN ALÁÌSÀN ÀTI ÀWỌN OUN ÈLÒ ÌMỌ̀ ÌṢÈGÙN*
10. *ALÁṢẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ KẸ́DÙN IKÚ DỌ̀TUN ỌLÁDIPỌ̀ TÍ Ó JẸ́ AKỌ̀RÒYÌN ORÍ Ẹ̀RỌ AYÉLUJÁRA TI EAGLE*
11. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ MÁA KÀN NÍPÁ FÚN ÀWỌN ILÉ Ẹ̀KỌ́ GÍGA, ILÉ ÌWÒSÀN ÌKỌNI LÁTI MÁA SAN OWÓ ORÍ ÀTI ÌDÍYELÉ INÁ MỌ̀NÀMỌ́NÁ*
12. *ÀTÍKÙ ÀBÚBÁKÀR ṢÌ TẸMPẸLẸ MỌ́Ọ PÉ ÒUN MÁA YỌ OWÓ ÌRÀNWỌ́ ORÍ EPO BÍ ÒUN BÁ GORÍ IPÒ ALÁṢẸ PẸ̀LÚ BÍ ÀWỌN ÈNÌYÀN ṢE Ń SỌ ÒGÚLÙTU Ọ̀RỌ̀ SÍI*
13. *ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀ṢUN TI DÁ ÀWỌN ÀFỌBAJẸ LỌ́WỌ́ KỌ́ LÁTI FÒPIN SÍ GBOGBO ÈTÒ YÍYAN ỌBA ÌLÚ KÓKÀ MÌÍRÀN LÁSÌKÒ YÌÍ*
14. *ÀWỌN AJÍNIGBÉ TI JÍ AWAKỌ̀ ILÉ IṢẸ́ DANGOTE GBÉ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN BẸ́Ẹ̀ NI ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ TI BẸ̀RẸ̀ IṢẸ́ LÁTI ṢÀWARÍ Ẹ̀*
15. *ỌMỌ OGÚN ỌDÚN KAN (20YEARS) ṢÁ BÀBÁ Ẹ̀ LÁDÀ PA NÍ ÌPÍNLẸ̀ ANAMBRA*
*OLÚWATÓBILỌ́BA DÁRAMỌ́LÁ (GLAMOURLADY)*
*LÓ Ń JÁBỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ FÚN ÌKÀNNÌ AMÓHÙNMÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN)*